7. “Àbá ẹyin ọmọ Ísírẹ́lìkò ha dàbí àwọn ọmọ Kúsì sí mi?”ni Olúwa wí.“Èmi kò ha ti mú Ísírẹ́lì gòkè láti ilẹ̀ Éjíbítì jáde wáàti àwọn Fílístínì láti ilẹ̀ Káfítórìàti àwọn Árámú láti kírì?
8. “Dájúdájú, ojú Olúwa Ọlọ́run ń bẹ̀lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀.Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀Ṣíbẹ̀ Èmi kò ni pa ilé Jákọ́bù run pátapáta,”ni Olúwa wí.
9. “Nítorí Èmi yóò pàṣẹ,Èmi yóò sì mi ilé Ísírẹ́lìní àárin àwọn orílẹ̀ èdèbí a ti ń jọ ọkàn nínú ajọ̀tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
10. Gbogbo àwọn ẹlẹ́sẹ̀ láàrin àwọn ènìyàn mini yóò ti ipa idà kúgbogbo àwọn ti ń wí péAburú kì yóò lé wa bá,bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́?A mú Ísírẹ́lì padà bọ̀ sípò.
11. “Ní ọjọ́ náà ní Èmi yóò gbéàgọ́ Dáfídì tí ó wó róÈmi yóò mọ odi rẹ̀ tí ó wóÈmi yóò sì sọ ahoro rẹ̀ di ìlúÈmi yóò sì kọ bí ó ti wà tẹ́lẹ̀
12. kí wọn le jógun ìyókù Édómùàti gbogbo orílẹ̀ èdè ti ń jẹ́ orúkọ mi,”ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.
13. “Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí,“Tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè báTí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn báÀwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀Tí yóò sì ṣàn láti ara àwọn òkè kékèké.