7. Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkèẹṣẹ̀ àwọn tí ó mú ìyìn rere ayọ̀ wá,tí wọ́n kéde àlàáfíà,tí ó mú ìyìn rere wá,tí ó kéde ìgbàlà,tí ó sọ fún Ṣíhónì pé,“Ọlọ́run rẹ ń jọba!”
8. Tẹ́tísílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn ṣókèwọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀.Nígbà tí Olúwa padà sí Ṣíhónì,wọn yóò rí i pẹ̀lú ojúu wọn.
9. Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀,ẹ̀yin ahoro Jérúsálẹ́mù,nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú,ó sì ti ra Jérúsálẹ́mù padà.
10. Olúwa yóò sí apá mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀ní ojú gbogbo orílẹ̀ èdè,àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò ríìgbàlà Ọlọ́run wa.