O. Daf 105:18-25 Yorùbá Bibeli (YCE)

18. Ẹsẹ ẹniti nwọn fi ṣẹkẹṣẹkẹ pa lara: a dè e ninu irin:

19. Titi igba ti ọ̀rọ rẹ̀ de: ọ̀rọ Oluwa dan a wò.

20. Ọba ranṣẹ, nwọn si tú u silẹ; ani ijoye awọn enia, o si jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.

21. O fi jẹ oluwa ile rẹ̀, ati ijoye gbogbo ini rẹ̀.

22. Lati ma ṣe akoso awọn ọmọ-alade rẹ̀ nipa ifẹ rẹ̀; ati lati ma kọ́ awọn igbimọ rẹ̀ li ọgbọ́n.

23. Israeli si wá si Egipti pẹlu; Jakobu si ṣe atipo ni ilẹ Hamu.

24. O si mu awọn enia rẹ̀ bi si i pipọ̀-pipọ̀; o si mu wọn lagbara jù awọn ọta wọn lọ.

25. O yi wọn li aiya pada lati korira awọn enia rẹ̀, lati ṣe arekereke si awọn iranṣẹ rẹ̀.

O. Daf 105