O. Daf 105:17-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. O rán ọkunrin kan lọ siwaju wọn; ani Josefu ti a tà li ẹrú:

18. Ẹsẹ ẹniti nwọn fi ṣẹkẹṣẹkẹ pa lara: a dè e ninu irin:

19. Titi igba ti ọ̀rọ rẹ̀ de: ọ̀rọ Oluwa dan a wò.

20. Ọba ranṣẹ, nwọn si tú u silẹ; ani ijoye awọn enia, o si jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.

21. O fi jẹ oluwa ile rẹ̀, ati ijoye gbogbo ini rẹ̀.

22. Lati ma ṣe akoso awọn ọmọ-alade rẹ̀ nipa ifẹ rẹ̀; ati lati ma kọ́ awọn igbimọ rẹ̀ li ọgbọ́n.

O. Daf 105