O. Daf 105:15-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Pe, Ẹ máṣe fi ọwọ kan ẹni-ororo mi ki ẹ má si ṣe awọn woli mi ni ibi,

16. Pẹlupẹlu o pè ìyan wá si ilẹ na: o ṣẹ́ gbogbo ọpá onjẹ.

17. O rán ọkunrin kan lọ siwaju wọn; ani Josefu ti a tà li ẹrú:

18. Ẹsẹ ẹniti nwọn fi ṣẹkẹṣẹkẹ pa lara: a dè e ninu irin:

19. Titi igba ti ọ̀rọ rẹ̀ de: ọ̀rọ Oluwa dan a wò.

20. Ọba ranṣẹ, nwọn si tú u silẹ; ani ijoye awọn enia, o si jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.

21. O fi jẹ oluwa ile rẹ̀, ati ijoye gbogbo ini rẹ̀.

O. Daf 105