Jer 30:21-24 Yorùbá Bibeli (YCE)

21. Ọlọla rẹ̀ yio si jẹ lati inu ara wọn wá, alakoso rẹ̀ lati ãrin rẹ̀; emi o si mu u sunmọ tosi, on o si sunmọ ọdọ mi: nitori tani ẹniti o mura ọkàn rẹ̀ lati sunmọ ọdọ mi? li Oluwa wi.

22. Ẹnyin o si jẹ enia mi, emi o si jẹ Ọlọrun nyin.

23. Wò o, afẹfẹ iji Oluwa! ibinu ti jade! afẹyika ìji yio ṣubu ni ikanra si ori oluṣe-buburu.

24. Ibinu kikan Oluwa kì o pada, titi on o fi ṣe e, ati titi on o fi mu èro ọkàn rẹ̀ ṣẹ: li ọjọ ikẹhin ẹnyin o mọ̀ ọ daju.

Jer 30