2. Kro 31:18-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

18. Ati fun awọn ti a kọ sinu iwe, gbogbo awọn ọmọ kekeke wọn, awọn aya wọn, ati awọn ọmọkunrin wọn, ati awọn ọmọbinrin wọn, ja gbogbo ijọ enia na: nitori ninu otitọ ni nwọn yà ara wọn si mimọ́ ninu iṣẹ mimọ́.

19. Ati fun awọn ọmọ Aaroni, awọn alufa, ti o wà li oko igberiko ilu wọn ni olukuluku ilu, awọn ọkunrin wà nibẹ, ti a pè li orukọ, lati ma fi fun gbogbo awọn ọkunrin ninu awọn alufa, ati fun gbogbo awọn ti a kà ni idile idile ninu awọn ọmọ Lefi.

20. Bayi ni Hesekiah si ṣe ni gbogbo Juda, o si ṣe eyiti o dara, ti o si tọ́, ti o si ṣe otitọ, niwaju Oluwa Ọlọrun rẹ̀.

21. Ati ninu gbogbo iṣẹ ti o bẹ̀rẹ ninu iṣẹ-ìsin ile Ọlọrun, ati ninu ofin, ati ni aṣẹ, lati wá Ọlọrun, o fi gbogbo ọkàn rẹ̀ ṣe e, o si ṣe rere.

2. Kro 31