2. Kro 3:1-8 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. SOLOMONI si bẹ̀rẹ si ikọ́ ile Oluwa ni Jerusalemu li òke Moriah nibiti Ọlọrun farahàn Dafidi baba rẹ̀, ti Dafidi ti pèse, nibi ilẹ-ipaka Ornani, ara Jebusi.

2. On si bẹ̀rẹ si ikọ́ ile ni ọjọ keji oṣù keji, li ọdun kẹrin ijọba rẹ̀.

3. Eyi si ni ìwọn ti Solomoni fi lelẹ fun kikọ́ ile Ọlọrun. Gigùn rẹ̀ ni igbọnwọ gẹgẹ bi ìwọn igbãni li ọgọta igbọnwọ, ati ibu rẹ̀, ogún igbọnwọ.

4. Ati iloro ti mbẹ niwaju ile na, gigùn rẹ̀ ri gẹgẹ bi ibu ile na, ogún igbọnwọ, ati giga rẹ̀ ọgọfa; o si fi kiki wura bò o ninu.

5. O si fi igi-firi bò ile ti o tobi, o si fi wura daradara bò o, o si gbẹ́ àworan igi-ọpẹ ati ẹ̀wọn si i.

6. O si fi okuta iyebiye ṣe ile na li ọṣọ́ fun ẹwà: wura na si jasi wura Parfaimu.

7. O si fi wura bò ile na pẹlu, ati ìti, opó, ati ogiri rẹ̀ wọnni, ati ilẹkun rẹ̀ mejeji; o si gbẹ́ àworan awọn kerubu si ara ogiri na.

8. O si ṣe ile mimọ́-jùlọ na, gigùn eyiti o wà gẹgẹ bi ibu ile na, ogún igbọnwọ: ati ibu rẹ̀, ogún igbọnwọ: o si fi wura daradara bò o, ti o to ẹgbẹta talenti.

2. Kro 3