2. Kro 2:15-18 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Njẹ nitorina alikama ati ọkà barli, ororo, ati ọti-waini na ti oluwa mi ti sọ, jẹ ki o fi ranṣẹ si awọn ọmọ-ọdọ rẹ̀.

16. Awa o si ké igi lati Lebanoni wá, iyekiye ti iwọ o fẹ; awa o si mu wọn fun ọ wá ni fifó li okun si Joppa; iwọ o si rù wọn gòke lọ si Jerusalemu.

17. Solomoni si kaye gbogbo awọn ajeji ọkunrin ti o wà ni ilẹ Israeli, gẹgẹ bi kikà ti Dafidi, baba rẹ̀ ti kà wọn; a si ri pe, nwọn jẹ ọkẹ-mẹjọ o di-egbejilelọgbọ̀n.

18. O si yàn ẹgbã marundilogoji ninu wọn lati ru ẹrù, ati ọkẹ mẹrin lati ṣe aké-okuta li ori òke, ati egbejidilogun alabojuto lati kó awọn enia ṣiṣẹ.

2. Kro 2