2. A. Ọba 8:25-29 Yorùbá Bibeli (YCE)

25. Li ọdun kejila Joramu ọmọ Ahabu ọba Israeli, Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ si ijọba.

26. Ẹni ọdun mejilelogun ni Ahasiah jẹ nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba; o si jọba li ọdun kan ni Jerusalemu. Orukọ iya rẹ̀ a si ma jẹ Ataliah, ọmọbinrin Omri ọba Israeli.

27. O si rìn li ọ̀na ile Ahabu, o si ṣe ibi niwaju Oluwa, bi ile Ahabu ti ṣe: nitoriti o nṣe ana ile Ahabu.

28. On si lọ pẹlu Joramu ọmọ Ahabu si ogun na ti o mba Hasaeli ọba Siria jà ni Ramoti-Gileadi; awọn ara Siria si ṣa Joramu li ọgbẹ́.

29. Joramu ọba si pada si Jesreeli lati wò ọgbẹ́ ti awọn ara Siria ti ṣa a ni Rama, nigbati o mba Hasaeli ọba Siria ja. Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda sọ̀kalẹ lati wá iwò Joramu ọmọ Ahabu ni Jesreeli nitoriti o nṣe aisàn.

2. A. Ọba 8