Gẹn 31:19-24 Yorùbá Bibeli (YCE)

19. Labani si lọ irẹrun agutan rẹ̀: Rakeli si ti jí awọn ere baba rẹ̀ lọ.

20. Jakobu si tàn Labani ara Siria jẹ, niti pe kò wi fun u ti o fi salọ.

21. Bẹ̃li o kó ohun gbogbo ti o ní salọ: o si dide, o si kọja odò, o si kọju rẹ̀ si oke Gileadi.

22. A si wi fun Labani ni ijọ́ kẹta pe, Jakobu salọ.

23. O si mú awọn arakunrin rẹ̀ pẹlu rẹ̀, o si lepa rẹ̀ ni ìrin ijọ́ meje: o si bá a li oke Gileadi.

24. Ọlọrun si tọ̀ Labani, ara Siria wá li oru li oju-alá, o si wi fun u pe, Kiyesi ara rẹ, ki iwọ ki o máṣe bá Jakobu sọ rere tabi buburu.

Gẹn 31