Esek 23:23-26 Yorùbá Bibeli (YCE)

23. Awọn ara Babiloni, ati gbogbo awọn ara Kaldea, Pekodu, ati Ṣoa, ati Koa, ati gbogbo awọn ara Assiria pẹlu wọn: gbogbo wọn jẹ ọmọkunrin ti o wunni, balogun ati awọn olori, awọn ọkunrin ti o li okiki, gbogbo wọn li o ngun ẹṣin.

24. Nwọn o si wá fi kẹkẹ́ ogun, kẹkẹ́ ẹrù, ati kekẹ́ kekeke doju kọ ọ, ati pẹlu ìgbajọ ọ̀pọ enia, awọn ti yio doju asà, ati apata, ati akoro kọ ọ niha gbogbo: emi o si gbe idajọ kalẹ niwaju wọn, nwọn o si da ọ lẹjọ gẹgẹ bi idajọ wọn.

25. Emi o si doju owu mi kọ ọ, nwọn o si fi irúnu ba ọ lò: nwọn o fá imu rẹ ati eti rẹ; ati awọn ti o kù ninu rẹ yio ti ọwọ́ idà ṣubu: nwọn o mu awọn ọmọ rẹ ọkunrin, ati awọn ọmọ rẹ obinrin lọ, ati awọn ti o kù ninu rẹ, li a o fi iná run.

26. Nwọn o si bọ aṣọ rẹ, nwọn o si mu ohun ọṣọ daradara rẹ lọ.

Esek 23