Deu 28:37-50 Yorùbá Bibeli (YCE)

37. Iwọ o si di ẹni iyanu, ati ẹni owe, ati ẹni ifisọrọsọ, ninu gbogbo orilẹ-ède, nibiti OLUWA yio gbé darí rẹ si.

38. Iwọ o mú irugbìn pupọ̀ lọ sinu oko, diẹ ni iwọ o si ri kójọ; nitoripe eṣú ni yio jẹ ẹ run.

39. Iwọ o gbìn ọgbà-àjara, iwọ o si ṣe itọju rẹ̀, ṣugbọn iwọ ki yio mu ninu ọti-waini rẹ̀, bẹ̃ni iwọ ki yio ká ninu eso-àjara rẹ̀, nitoripe kòkoro ni yio fi wọn jẹ.

40. Iwọ o ní igi olifi ni gbogbo àgbegbe rẹ, ṣugbọn iwọ ki yio fi oróro para; nitoripe igi olifi rẹ yio rẹ̀danu.

41. Iwọ o bi ọmọkunrin ati ọmọbinrin, ṣugbọn nwọn ki yio jẹ́ tirẹ; nitoripe nwọn o lọ si oko-ẹrú.

42. Gbogbo igi rẹ ati eso ilẹ rẹ yio jẹ́ ti eṣú.

43. Alejò ti mbẹ lãrin rẹ, yio ma ga jù ọ lọ siwaju ati siwaju, iwọ o si ma di ẹni irẹsilẹ, siwaju ati siwaju.

44. On ni yio ma wín ọ, iwọ ki yio si wín i: on ni yio ma ṣe ori, iwọ o si ma ṣe ìru.

45. Gbogbo egún wọnyi yio si wá sori rẹ, yio si lepa rẹ, yio si bá ọ, titi iwọ o fi run; nitoriti iwọ kò fetisi ohùn OLUWA Ọlọrun rẹ, lati pa aṣẹ rẹ̀ ati ìlana rẹ̀ mọ́ ti o palaṣe fun ọ.

46. Nwọn o si wà lori rẹ fun àmi ati fun iyanu, ati lori irú-ọmọ rẹ lailai:

47. Nitoriti iwọ kò fi àyọ sìn OLUWA Ọlọrun rẹ, ati inudidun, nitori ọ̀pọ ohun gbogbo:

48. Nitorina ni iwọ o ṣe ma sìn awọn ọtá rẹ ti OLUWA yio rán si ọ, ninu ebi, ati ninu ongbẹ, ati ninu ìhoho, ati ninu ainí ohun gbogbo: on o si fi àjaga irin bọ̀ ọ li ọrùn, titi yio fi run ọ.

49. OLUWA yio gbé orilẹ-ède kan dide si ọ lati ọ̀na jijìn, lati opin ilẹ wa bi idì ti ifò; orilẹ-ède ti iwọ ki yio gbọ́ ède rẹ̀;

50. Orilẹ-ède ọdaju, ti ki yio ṣe ojuṣaju arugbo, ti ki yio si ṣe ojurere fun ewe:

Deu 28