Orin Dafidi 97:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Àwọn ará Sioni gbọ́, inú wọn dùn.Àwọn ará ìlú Juda sì ń yọ̀,nítorí ìdájọ́ rẹ, OLUWA.

9. Nítorí ìwọ OLUWA ni Ọ̀gá Ògo,o ju gbogbo ayé lọ,a gbé ọ ga ju gbogbo oriṣa lọ.

10. Ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn OLUWA, ẹ kórìíra ibi;OLUWA á máa dá ẹ̀mí àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ sí,a sì máa gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn eniyan burúkú.

11. Ìmọ́lẹ̀ á máa tàn fún àwọn olódodo,ayọ̀ sì wà fún àwọn olótìítọ́ inú.

12. Ẹ máa yọ̀ ninu OLUWA, ẹ̀yin olódodo,kí ẹ sì máa yin orúkọ mímọ́ rẹ̀.

Orin Dafidi 97