Orin Dafidi 96:5-9 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Nítorí oriṣa lásán ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù ń sìn,ṣugbọn OLUWA ni ó dá ọ̀run.

6. Iyì ati ọlá ńlá ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀;agbára ati ẹwà kún inú ilé mímọ́ rẹ̀.

7. Ẹ yin OLUWA, gbogbo ẹ̀yin aráyé;ẹ kókìkí ògo ati agbára rẹ̀.

8. Ẹ fún OLUWA ní iyì tí ó tọ́ sí orúkọ rẹ̀,ẹ mú ọrẹ lọ́wọ́ wá sinu àgbàlá rẹ̀.

9. Ẹ sin OLUWA ninu ẹwà ìwà mímọ́;gbogbo ayé, ẹ wárìrì níwájú rẹ̀.

Orin Dafidi 96