Orin Dafidi 90:5-10 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ìwọ a máa gbá ọmọ eniyan dànù; wọ́n dàbí àlá,bíi koríko tí ó tutù ní òwúrọ̀;

6. ní òwúrọ̀ á máa gbilẹ̀, á sì máa jí pérépéré;ní ìrọ̀lẹ́ á sá, á sì rọ.

7. Ibinu rẹ pa wá run;ìrúnú rẹ sì bò wá mọ́lẹ̀.

8. O ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa kalẹ̀ ní iwájú rẹ;àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìkọ̀kọ̀ wa sì hàn kedere ninu ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.

9. Nítorí ọjọ́ ayé wa ń kọjá lọ ninu ibinu rẹ;ayé wa sì ń dópin bí ẹni mí kanlẹ̀.

10. Aadọrin ọdún ni ọjọ́ ayé wa;pẹlu ipá a lè tó ọgọrin;sibẹ gbogbo rẹ̀ jẹ́ kìkì làálàá ati ìyọnu;kíá, ayé wa á ti dópin, ẹ̀mí wa á sì fò lọ.

Orin Dafidi 90