Orin Dafidi 90:1-7 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA, ìwọ ni o ti jẹ́ ibi ààbò wa láti ìrandíran.

2. Kí o tó dá àwọn òkè,ati kí o tó dá ilẹ̀ ati ayé,láti ayérayé, ìwọ ni Ọlọrun.

3. O sọ eniyan di erùpẹ̀ pada,o sì wí pé, “Ẹ yipada, ẹ̀yin ọmọ eniyan.”

4. Nítorí pé lójú rẹ, ẹgbẹrun ọdún dàbí àná,tabi bí ìṣọ́ kan ní òru.

5. Ìwọ a máa gbá ọmọ eniyan dànù; wọ́n dàbí àlá,bíi koríko tí ó tutù ní òwúrọ̀;

6. ní òwúrọ̀ á máa gbilẹ̀, á sì máa jí pérépéré;ní ìrọ̀lẹ́ á sá, á sì rọ.

7. Ibinu rẹ pa wá run;ìrúnú rẹ sì bò wá mọ́lẹ̀.

Orin Dafidi 90