Orin Dafidi 89:30-34 BIBELI MIMỌ (BM)

30. “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀,tí wọn kò sì tẹ̀lé ìlànà mi,

31. bí wọ́n bá tàpá sí àṣẹ mi,tí wọn kò sì pa òfin mi mọ́;

32. n óo nà wọ́n lẹ́gba nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,n óo sì nà wọ́n ní pàṣán nítorí àìdára wọn.

33. Ṣugbọn ìfẹ́ mi tí kì í yẹ̀ kò ní kúrò lára rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni n kò ní yẹ òtítọ́ mi.

34. N kò ni yẹ majẹmu mi,bẹ́ẹ̀ ni n kò ní yí ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ pada.

Orin Dafidi 89