Orin Dafidi 87:2-6 BIBELI MIMỌ (BM)

2. OLUWA fẹ́ràn ẹnubodè Sioni ju gbogbo ìlúyòókù lọ ní ilẹ̀ Jakọbu.

3. Ọpọlọpọ nǹkan tó lógo ni a sọ nípa rẹ,ìwọ ìlú Ọlọrun.

4. Tí mo bá ń ka àwọn ilẹ̀ tí ó mọ rírì mi,n óo dárúkọ Ijipti ati Babiloni,Filistia ati Tire, ati Etiopia.Wọn á máa wí pé, “Ní Jerusalẹmu ni wọ́n ti bí eléyìí.”

5. A óo wí nípa Sioni pé,“Ibẹ̀ ni a ti bí eléyìí ati onítọ̀hún,”nítorí pé Ọ̀gá Ògo yóo fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀.

6. OLUWA yóo ṣírò rẹ̀ mọ́ wọnnígbà tí ó bá ń ṣe àkọsílẹ̀ àwọn eniyan rẹ̀ pé,“Ní Sioni ni a ti bí eléyìí.”

Orin Dafidi 87