Orin Dafidi 78:65-70 BIBELI MIMỌ (BM)

65. Lẹ́yìn náà, OLUWA dìde bí ẹni tají lójú oorun,bí ọkunrin alágbára tí ó mu ọtí yó tí ó ń kígbe.

66. Ó lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ sẹ́yìn;ó dójú tì wọ́n títí ayé.

67. Ó kọ àgọ́ àwọn ọmọ Josẹfu sílẹ̀;kò sì yan ẹ̀yà Efuraimu;

68. ṣugbọn ó yan ẹ̀yà Juda,ó sì yan òkè Sioni tí ó fẹ́ràn.

69. Níbẹ̀ ni ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀ tí ó ga bí ọ̀run sí,ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ bí ayé títí lae.

70. Ó yan Dafidi iranṣẹ rẹ̀;ó sì mú un láti inú agbo ẹran.

Orin Dafidi 78