Orin Dafidi 78:26-30 BIBELI MIMỌ (BM)

26. Ó mú kí afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn fẹ́ ní ojú ọ̀run,ó sì fi agbára rẹ̀ darí afẹ́fẹ́ ìhà gúsù;

27. ó sì rọ̀jò ẹran sílẹ̀ fún wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀;àní, ẹyẹ abìyẹ́ bíi yanrìn etí òkun.

28. Ó mú kí wọn bọ́ sílẹ̀ láàrin ibùdó;yíká gbogbo àgọ́ wọn,

29. Àwọn eniyan náà jẹ, wọ́n sì yó;nítorí pé Ọlọrun fún wọn ní ohun tí ọkàn wọn fẹ́.

30. Ṣugbọn kí wọn tó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn wọn lọ́rùn,àní, nígbà tí wọn ṣì ń jẹun lọ́wọ́.

Orin Dafidi 78