Orin Dafidi 78:20-24 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Lóòótọ́ ó lu òkúta tí omi fi tú jáde,tí odò sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn.Ṣé ó lè fún wa ní òkèlè pẹlu,àbí ó lè pèsè ẹran fún àwọn eniyan rẹ̀?”

21. Nítorí náà nígbà tí OLUWA gbọ́,inú bí i;iná mọ́ ìdílé Jakọbu,inú OLUWA sì ru sí àwọn ọmọ Israẹli;

22. nítorí pé wọn kò gba Ọlọrun gbọ́;wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé agbára ìgbàlà rẹ̀.

23. Sibẹ ó pàṣẹ fún ìkùukùu lókè,ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀.

24. Ó rọ òjò mana sílẹ̀fún wọn láti jẹ,ó sì fún wọn ní ọkà ọ̀run.

Orin Dafidi 78