Orin Dafidi 74:18-21 BIBELI MIMỌ (BM)

18. OLUWA, ranti pé àwọn ọ̀tá ń fi ọ́ ṣe yẹ̀yẹ́;àwọn òmùgọ̀ eniyan sì ń fi orúkọ rẹ ṣe ẹlẹ́yà.

19. Má fi ẹ̀mí àwa àdàbà rẹ lé àwọn ẹranko lọ́wọ́;má sì gbàgbé àwa eniyan rẹ tí ìyà ń jẹ títí lae.

20. Ranti majẹmu rẹ;nítorí pé gbogbo kọ̀rọ̀ ilẹ̀ wa kún fún ìwà ipá.

21. Má jẹ́ kí ojú ti àwọn tí à ń pọ́n lójú;jẹ́ kí àwọn tí ìyà ń jẹ ati àwọn aláìní máa yin orúkọ rẹ.

Orin Dafidi 74