Orin Dafidi 69:24-31 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Rọ òjò ibinu rẹ lé wọn lórí,kí o sì jẹ́ kí wọ́n rí gbígbóná ibinu rẹ.

25. Kí ibùdó wọn ó di ahoro,kí ẹnikẹ́ni má sì gbé inú àgọ́ wọn.

26. Nítorí ẹni tí o ti kọlù ni wọ́n tún gbógun tì;ẹni tí o ti ṣá lọ́gbẹ́ ni wọ́n sì tún ń pọ́n lójú.

27. Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn;má sì jẹ́ kí wọ́n rí ìdáláre lọ́dọ̀ rẹ.

28. Pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò ninu ìwé ìyè;kí á má sì kọ orúkọ wọn mọ́ ti àwọn olódodo.

29. Ojú ń pọ́n mi, mo sì ń jẹ̀rora;Ọlọrun, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè!

30. Èmi ó fi orin yin orúkọ Ọlọrun;n óo fi ọpẹ́ gbé e ga.

31. Èyí yóo tẹ́ Ọlọrun lọ́rùn ju akọ mààlúù lọ,àní, akọ mààlúù tòun tìwo ati pátákò rẹ̀.

Orin Dafidi 69