Orin Dafidi 66:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Gbogbo ayé, ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọrun.

2. Ẹ kọ orin ògo yin orúkọ rẹ̀;ẹ yìn ín, ẹ fògo fún un!

3. Ẹ sọ fún Ọlọrun pé,“Iṣẹ́ rẹ bani lẹ́rù pupọ,agbára rẹ pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́,tí àwọn ọ̀tá rẹ fi ń fi ìbẹ̀rù tẹríba fún ọ.

4. Gbogbo ayé ní ń sìn ọ́;wọ́n ń kọ orin ìyìn fún ọ,wọ́n ń kọ orin ìyìn sí orúkọ rẹ.”

Orin Dafidi 66