6. Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ ninu ilé mímọ́ rẹ̀,ó ní, “Tayọ̀tayọ̀ ni n óo fi pín Ṣekemu,n óo sì pín àfonífojì Sukotu.
7. Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase;Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi,Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
8. Moabu ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi;lórí Edomu ni n óo bọ́ bàtà mi lé;n óo sì hó ìhó ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistia.”
9. Ta ni yóo mú mi wọ inú ìlú olódi náà?Ta ni yóo mú mi lọ sí Edomu?
10. Ọlọrun, o kò ha ti kọ̀ wá sílẹ̀?Ọlọrun, o ò bá àwọn ọmọ ogun wa jáde lọ sójú ogun mọ́.
11. Ràn wá lọ́wọ́, bá wa gbógun ti àwọn ọ̀tá wa,nítorí pé asán ni ìrànlọ́wọ́ eniyan.
12. Pẹlu àtìlẹ́yìn Ọlọrun a óo ṣe akin,nítorí òun ni yóo tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.