Orin Dafidi 37:25-29 BIBELI MIMỌ (BM)

25. Mo ti jẹ́ ọmọde rí; mo sì ti dàgbà:n kò tíì ri kí á kọ olódodo sílẹ̀,tabi kí ọmọ rẹ̀ máa tọrọ jẹ.

26. Olódodo ní ojú àánú, a sì máa yáni ní nǹkan,ayọ̀ ń bẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀.

27. Ẹ yẹra fún ibi; ẹ sì máa ṣe rere;kí ẹ lè wà ní ààyè yín títí lae.

28. Nítorí OLUWA fẹ́ràn ẹ̀tọ́;kò ní kọ àwọn olùfọkànsìn rẹ̀ sílẹ̀.Yóo máa ṣọ́ wọn títí lae,ṣugbọn a óo pa àwọn ọmọ eniyan burúkú run.

29. Àwọn ẹni rere ni yóo jogún ilẹ̀ náà;wọn óo sì máa gbé orí rẹ̀ títí lae.

Orin Dafidi 37