Orin Dafidi 36:9-12 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni orísun ìyè wà;ninu ìmọ́lẹ̀ rẹ ni a ti ń rí ìmọ́lẹ̀.

10. Túbọ̀ máa fi ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀han àwọn tí ó mọ̀ ọ́,sì máa fi òdodo rẹ han àwọn ọlọ́kàn mímọ́.

11. Má jẹ́ kí àwọn agbéraga borí mi,má sì jẹ́ kí àwọn eniyan burúkú lé mi kúrò.

12. Ẹ wo àwọn aṣebi níbi tí wọ́n ṣubú sí;wọ́n dà wólẹ̀, wọn kò sì le dìde.

Orin Dafidi 36