17. Nígbà tí olódodo bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́, OLUWA a máa gbọ́,a sì máa gbà wọ́n kúrò ninu gbogbo ìyọnu wọn.
18. OLUWA wà nítòsí àwọn tí ọkàn wọn bàjẹ́,a sì máa gba àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn là.
19. Ìpọ́njú olódodo a máa pọ̀;ṣugbọn OLUWA a máa kó o yọ ninu gbogbo wọn.
20. A máa pa gbogbo egungun rẹ̀ mọ́;kì í jẹ́ kí ọ̀kankan fọ́ ninu wọn.
21. Ibi ni yóo pa eniyan burúkú;a óo sì dá àwọn tí ó kórìíra olódodo lẹ́bi.
22. OLUWA ra ẹ̀mí àwọn iranṣẹ rẹ̀ pada;ẹnikẹ́ni tí ó bá sá di í kò ní jẹ̀bi.