Orin Dafidi 32:5-9 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún ọ;n kò sì fi àìdára mi pamọ́ fún ọ.Mo ní, “Èmi óo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Oluwa,”o sì dáríjì mí.

6. Nítorí náà, kí gbogbo olódodo máa gbadura sí ọ;ní àkókò tí ìpọ́njú bá ń yí lura wọn bí ìṣàn omi ńlá,kò ní dé ọ̀dọ̀ wọn.

7. Ìwọ ni ibi ìsásí mi;o pa mí mọ́ kúrò ninu ìṣòro;o sì fi ìgbàlà yí mi ká.

8. N óo kọ́ ọ, n óo sì tọ́ ọ sí ọ̀nà tí o óo rìn;n óo máa gbà ọ́ ní ìmọ̀ràn;n óo sì máa mójútó ọ.

9. Má ṣe dàbí ẹṣin tabi ìbaaka,tí kò ni ọgbọ́n ninu,tí a gbọdọ̀ kó ìjánu sí lẹ́nukí ó tó lè gbọ́ ti oluwa rẹ̀.

Orin Dafidi 32