Orin Dafidi 31:15-24 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ;gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi,ati lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi.

16. Jẹ́ kí èmi iranṣẹ rẹ rí ojurere rẹ,gbà mí là, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.

17. Má jẹ́ kí ojú tì mí, OLUWA,nítorí ìwọ ni mò ń ké pè.Jẹ́ kí ojú ti àwọn eniyan burúkú;jẹ́ kí ẹnu wọn wọ wòwò títí wọ ibojì.

18. Jẹ́ kí àwọn òpùrọ́ yadi,àní àwọn tí ń fi ìgbéraga ati ẹ̀gàn sọ̀rọ̀ àìdára nípa olódodo.

19. Háà! Ohun rere mà pọ̀ lọ́wọ́ rẹ otí o ti sọ lọ́jọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,tí o sì ti pèsè ní ìṣojú àwọn ọmọ eniyan,fún àwọn tí ó sá di ọ́.

20. O fi ìyẹ́ apá rẹ ṣíji bò wọ́n;o pa wọ́n mọ́ kúrò ninu rìkíṣí àwọn eniyan;o sì pa wọ́n mọ́ lábẹ́ ààbò rẹ,kúrò lọ́wọ́ ẹnu àwọn ẹlẹ́jọ́ wẹ́wẹ́.

21. Ẹni ìyìn ni OLUWA, nítorí pé, lọ́nà ìyanu,ó fi ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ hàn mí,nígbà tí ilẹ̀ ká mi mọ́.

22. Ẹ̀rù bà mí, mo sì sọ pé,“A lé mi jìnnà kúrò ní iwájú rẹ.”Ṣugbọn o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ minígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.

23. Ẹ fẹ́ràn OLUWA, gbogbo ẹ̀yin olódodo,OLUWA a máa ṣọ́ àwọn olóòótọ́,a sì máa san àlékún ẹ̀san fún àwọn agbéraga.

24. Ẹ múra gírí, kí ẹ sì mọ́kàn le,gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé OLUWA.

Orin Dafidi 31