Orin Dafidi 28:6-9 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Ẹni ìyìn ni OLUWA!Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

7. OLUWA ni agbára ati asà mi,òun ni mo gbẹ́kẹ̀lé;ó ràn mí lọ́wọ́, ọkàn mi sì kún fún ayọ̀;mo sì fi orin ìyìn dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀.

8. OLUWA ni agbára àwọn eniyan rẹ̀;òun ni ààbò ìgbàlà fún ẹni àmì òróró rẹ̀.

9. Gba àwọn eniyan rẹ là, OLUWA,kí o sì bukun ilẹ̀ ìní rẹ.Jẹ́ olùṣọ́-aguntan wọn,kí o sì máa tọ́jú wọn títí lae.

Orin Dafidi 28