Orin Dafidi 28:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ìwọ ni mo kígbe pè, OLUWA,ìwọ ni ààbò mi, má di etí sí mi.Nítorí bí o bá dákẹ́ sí min óo dàbí àwọn òkú, tí wọ́n ti lọ sinu kòtò.

2. Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi,bí mo ti ń kígbe sí ọ pé kí o ràn mí lọ́wọ́;tí mo gbé ọwọ́ mi sókèsí ìhà ilé mímọ́ rẹ.

3. Má ṣe kó mi lọ pẹlu àwọn eniyan burúkú,pẹlu àwọn tí ń ṣe iṣẹ́ ibi,àwọn tí ń bá àwọn aládùúgbò wọnsọ ọ̀rọ̀ alaafia,ṣugbọn tí ètekéte ń bẹ ninu ọkàn wọn.

4. San án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn,àní gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ burúkú wọn;san án fún wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn,fún wọn ní èrè tí ó tọ́ sí wọn.

Orin Dafidi 28