Orin Dafidi 19:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ìlànà OLUWA tọ́, ó ń mú ọkàn yọ̀,àṣẹ OLUWA péye, a máa lani lójú.

9. Ìbẹ̀rù OLUWA pé, ó wà títí lae,ìdájọ́ OLUWA tọ́, òdodo ni gbogbo wọn.

10. Wọ́n wuni ju wúrà lọ,àní ju ojúlówó wúrà lọ;wọ́n sì dùn ju oyin,àní, wọ́n dùn ju oyin tí ń kán láti inú afárá lọ.

11. Pẹlupẹlu àwọn ni wọ́n ń ki èmi iranṣẹ rẹ, nílọ̀,èrè pupọ sì ń bẹ ninu pípa wọ́n mọ́.

12. Ṣugbọn ta ni lè mọ àṣìṣe ara rẹ̀?Wẹ̀ mí mọ́ ninu àṣìṣe àìmọ̀ mi.

Orin Dafidi 19