Orin Dafidi 18:15-23 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Nígbà náà ni ìsàlẹ̀ òkun hàn ketekete,ìpìlẹ̀ ayé sì fojú hàn gbangba nítorí ìbáwí rẹ, OLUWA,ati nítorí agbára èémí ihò imú rẹ.

16. Ó nawọ́ láti òkè wá, ó sì dì mí mú,ó fà mí jáde láti inú ibú omi.

17. Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi tí ó lágbára,ati lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi;nítorí wọ́n lágbára jù mí lọ.

18. Wọ́n gbógun tì mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi,ṣugbọn OLUWA ni aláfẹ̀yìntì mi.

19. Ó mú mi jáde wá síbi tí ó láàyè,ó yọ mí jáde nítorí tí inú rẹ̀ dùn sí mi.

20. OLUWA ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,bí ọwọ́ mi ṣe mọ́ ni ó ṣe pín mi lérè.

21. Nítorí tí mo ti pa ọ̀nà OLUWA mọ́,n kò ṣe ibi nípa yíyà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun mi.

22. Nítorí pé gbogbo òfin rẹ̀ ni mo tẹ̀lé,n kò sì yà kúrò ninu ìlànà rẹ̀.

23. Mo wà ní àìlẹ́bi níwájú rẹ̀,mo sì ti yẹra fún ẹ̀ṣẹ̀.

Orin Dafidi 18