Orin Dafidi 144:2-5 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Òun ni àpáta mi, ààbò mi, odi mi, olùdáǹdè mi,asà mi, ẹni tí mo sá di.Òun ni ó tẹrí àwọn eniyan ba lábẹ́ rẹ̀.

3. OLUWA, kí ni eniyan jẹ́, tí o fi ń náání rẹ̀?Kí sì ni ọmọ eniyan tí o fi ń ranti rẹ̀?

4. Eniyan dàbí èémí,ọjọ́ ayé rẹ̀ sì dàbí òjìji tí ń kọjá lọ.

5. OLUWA, fa ojú ọ̀run wá sílẹ̀, kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá,fọwọ́ kan àwọn òkè ńlá, kí wọ́n máa rú èéfín.

Orin Dafidi 144