Orin Dafidi 139:14-20 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Mo yìn ọ́, nítorí pé ẹ̀rù jẹ̀jẹ̀ ati ẹni ìyanu ni ọ́;ìyanu ni iṣẹ́ ọwọ́ rẹ!O mọ̀ mí dájú.

15. Nígbà tí à ń ṣẹ̀dá egungun mi lọ́wọ́ ní ìkọ̀kọ̀,tí ẹlẹ́dàá ṣẹ̀ṣẹ̀ ń ṣọnà sí mi lára ní àṣírí,kò sí èyí tí ó pamọ́ fún ọ.

16. Kí á tó dá mi tán ni o ti rí mi,o ti kọ iye ọjọ́ tí a pín fún misinu ìwé rẹ,kí ọjọ́ ayé mi tilẹ̀ tó bẹ̀rẹ̀ rárá.

17. Ọlọrun, iyebíye ni èrò rẹ lójú mi!Wọ́n pọ̀ pupọ ní iye.

18. Bí mo bá ní kí n kà wọ́n,wọ́n pọ̀ ju iyanrìn lọ;nígbà tí mo bá sì jí,ọ̀dọ̀ rẹ náà ni n óo wà.

19. Ọlọrun, ò bá jẹ́ pa àwọn eniyan burúkú,kí àwọn apànìyàn sì kúrò lọ́dọ̀ mi.

20. Wọ́n ń sọ ọ̀rọ̀ ọ̀tẹ̀ nípa rẹ,àwọn ọ̀tá rẹ ń ba orúkọ rẹ jẹ́.

Orin Dafidi 139