Orin Dafidi 135:9-13 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Ẹni tí ó rán iṣẹ́ abàmì ati iṣẹ́ ìyanu sí ilẹ̀ Ijipti,ó rán sí Farao ati gbogbo àwọn iranṣẹ rẹ̀.

10. Ẹni tí ó pa orílẹ̀-èdè pupọ run;ó pa àwọn ọba alágbára:

11. Sihoni ọba àwọn Amori,Ogu ọba Baṣani,ati gbogbo ọba ilẹ̀ Kenaani.

12. Ó pín ilẹ̀ wọn fún àwọn eniyan rẹ̀;ó pín in fún Israẹli bí ohun ìní wọn.

13. OLUWA, orúkọ rẹ yóo wà títí lae,òkìkí rẹ óo sì máa kàn títí ayé.

Orin Dafidi 135