Orin Dafidi 135:4-7 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Nítorí pé OLUWA ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀,ó ti yan Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.

5. Èmi mọ̀ pé OLUWA tóbi,ati pé ó ju gbogbo oriṣa lọ.

6. Bí ó ti wu OLUWA ni ó ń ṣelọ́run ati láyé,ninu òkun ati ninu ibú.

7. Òun ló gbá ìkùukùu jọ láti òpin ilẹ̀ ayé,ó fi mànàmáná fún òjò,ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti inú ilé ìṣúra rẹ̀.

Orin Dafidi 135