Orin Dafidi 119:70-79 BIBELI MIMỌ (BM)

70. Ọkàn wọn ti yigbì,ṣugbọn èmi láyọ̀ ninu òfin rẹ.

71. Ìpọ́njú tí mo rí ṣe mí ní anfaani,ó mú kí n kọ́ nípa ìlànà rẹ.

72. Òfin rẹ níye lórí fún mi,ó ju ẹgbẹẹgbẹrun wúrà ati fadaka lọ.

73. Ìwọ ni o mọ mí, ìwọ ni o dá mi,fún mi ní òye kí n lè kọ́ òfin rẹ.

74. Inú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yóo máa dùnnígbà tí wọ́n bá rí mi,nítorí pé mo ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ.

75. OLUWA, mo mọ̀ pé ìdájọ́ rẹ tọ̀nà,ati pé lórí ẹ̀tọ́ ni o pọ́n mi lójú.

76. Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ máa tù mí ninu,gẹ́gẹ́ bí ìlérí tí o ṣe fún èmi, iranṣẹ rẹ.

77. Ṣàánú mi, kí n lè wà láàyè,nítorí pé òfin rẹ ni ìdùnnú mi.

78. Jẹ́ kí ojú ó ti àwọn onigbeeraga,nítorí wọ́n ṣe àrékérekè sí mi láìnídìí;ní tèmi, n óo máa ṣe àṣàrò lórí òfin rẹ.

79. Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ tọ̀ mí wá,kí wọ́n lè mọ òfin rẹ.

Orin Dafidi 119