Orin Dafidi 119:123-132 BIBELI MIMỌ (BM)

123. Mo fojú sọ́nà títí, agara dá mi,níbi tí mo tí ń retí ìgbàlà rẹ,ati ìmúṣẹ ìlérí òdodo rẹ.

124. Ṣe sí èmi iranṣẹ rẹ, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,kí o sì kọ́ mi ní ìlànà rẹ.

125. Iranṣẹ rẹ ni mí,fún mi lóye, kí n lè mọ ìlànà rẹ.

126. OLUWA, ó tó àkókò fún ọ láti ṣe nǹkankan,nítorí àwọn eniyan ń rú òfin rẹ.

127. Nítorí náà ni èmi ṣe fẹ́ràn òfin rẹju wúrà lọ; àní, ju ojúlówó wúrà.

128. Nítorí náà, èmi ń tẹ̀lé gbogbo ẹ̀kọ́ rẹ,mo sì kórìíra gbogbo ọ̀nà èké.

129. Òfin rẹ dára,nítorí náà ni mo ṣe ń pa wọ́n mọ́.

130. Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ a máa fúnni ní ìmọ́lẹ̀,a sì máa fi òye fún àwọn onírẹ̀lẹ̀.

131. Mo la ẹnu, mò ń mí hẹlẹ,nítorí pé mò ń lépa òfin rẹ.

132. Kọjú sí mi kí o ṣe mí lóorebí o ti máa ń ṣesí àwọn tí ó fẹ́ràn rẹ.

Orin Dafidi 119