Orin Dafidi 119:114-120 BIBELI MIMỌ (BM)

114. Ìwọ ni ibi ìpamọ́ mi ati asà mi,mo ní ìrètí ninu ọ̀rọ̀ rẹ.

115. Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin aṣebi,kí n lè pa òfin Ọlọrun mi mọ́.

116. Gbé mi ró gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, kí n lè wà láàyè,má sì dójú ìrètí mi tì mí.

117. Gbé mi ró, kí n lè wà láìléwu,kí n lè máa ka ìlànà rẹ sí nígbà gbogbo.

118. O ti kọ gbogbo àwọn tí ó yapa kúrò ninu ìlànà rẹ sílẹ̀,nítorí pé asán ni gbogbo ẹ̀tàn wọn.

119. O ti pa àwọn eniyan burúkú tì, bí ìdàrọ́ irin,nítorí náà ni mo ṣe fẹ́ràn ìlànà rẹ.

120. Mo wárìrì nítorí pé mo bẹ̀rù rẹ,mo sì bẹ̀rù ìdájọ́ rẹ.

Orin Dafidi 119