Orin Dafidi 114:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà tí Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ijipti,tí àwọn ọmọ Jakọbu jáde kúrò láàrin àwọn tí ń sọ èdè àjèjì,

2. Juda di ilé mímọ́ rẹ̀,Israẹli sì di ìjọba rẹ̀.

3. Òkun rí i, ó sá,Jọdani rí i, ó pada sẹ́yìn.

4. Àwọn òkè ńláńlá ń fò bí àgbò,àwọn òkè kéékèèké ń fò bí ọmọ aguntan.

Orin Dafidi 114