Orin Dafidi 109:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Má dákẹ́, ìwọ Ọlọrun tí mò ń yìn.

2. Nítorí pé ẹnu àwọn eniyan burúkú ati tiàwọn ẹlẹ́tàn kò dákẹ́,wọ́n ń sọ̀rọ̀ èké nípa mi.

3. Wọ́n ń sọ ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ káàkiri nípa mi,wọ́n sì ń gbógun tì mí láìnídìí.

4. Èmi fẹ́ràn wọn; ṣugbọn ẹ̀sùn ni wọ́n fi ń kàn mí,sibẹ, adura ni mò ń gbà fún wọn.

5. Ibi ni wọ́n fí ń san oore fún mi,ìkórìíra ni wọ́n sì fi ń san ìfẹ́ tí mo ní sí wọn.

Orin Dafidi 109