Orin Dafidi 105:39-45 BIBELI MIMỌ (BM)

39. OLUWA ta ìkùukùu bò wọ́n,ó sì pèsè iná láti tan ìmọ́lẹ̀ fún wọn lóru.

40. Wọ́n bèèrè ẹran, ó fún wọn ní àparò,ó sì pèsè oúnjẹ àjẹtẹ́rùn fún wọn láti ọ̀run.

41. Ó la àpáta, omi tú jáde,ó sì ṣàn ninu aṣálẹ̀ bí odò.

42. Nítorí pé ó ranti ìlérí mímọ́ rẹ̀,ati Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀.

43. Ó fi ayọ̀ kó àwọn eniyan rẹ̀ jáde,ó kó àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ jáde pẹlu orin.

44. Ó fún wọn ní ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn,wọ́n sì jogún èrè iṣẹ́ àwọn eniyan náà.

45. Kí wọ́n lè máa mú àṣẹ rẹ̀ ṣẹ,kí wọ́n sì máa pa òfin rẹ̀ mọ́.Ẹ yin OLUWA!

Orin Dafidi 105