16. Nígbà kan, ó mú kí ìyàn jà ní ilẹ̀ náà:ó ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ mọ́ wọn lẹ́nu.
17. Ṣugbọn ó kọ́ rán ọkunrin kan ṣáájú wọn,Josẹfu, ẹni tí a tà lẹ́rú.
18. Wọ́n so ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ mọ́ ọn lẹ́sẹ̀,wọ́n ti ọrùn rẹ̀ bọ irin,
19. títí ìgbà tí ohun tí ó sọ fi ṣẹ,tí OLUWA sì jẹ́rìí sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
20. Ọba ranṣẹ pé kí wọ́n tú u sílẹ̀,aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè sì dá a sílẹ̀.
21. Ó fi jẹ aláṣẹ ilé rẹ̀,ati alákòóso gbogbo nǹkan ìní rẹ̀;
22. láti máa ṣe olórí àwọn ìjòyè rẹ̀,kí ó sì máa kọ́ àwọn àgbà ìlú ní ìmọ̀.
23. Lẹ́yìn náà, Israẹli dé sí Ijipti,Jakọbu ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Hamu.