Orin Dafidi 102:7-11 BIBELI MIMỌ (BM)

7. Mo dùbúlẹ̀ láìlè sùn,mo dàbí ẹyẹ tí ó dá wà lórí òrùlé.

8. Àwọn ọ̀tá ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́ tọ̀sán-tòru,àwọn tí wọn ń pẹ̀gàn mi ń fi orúkọ mi ṣépè.

9. Mò ń jẹ eérú bí oúnjẹ,mo sì ń mu omijé mọ́ omi

10. nítorí ìrúnú ati ibinu rẹ;o gbé mi sókè,o sì jù mí nù.

11. Ọjọ́ ayé mi ń lọ bí òjìji àṣáálẹ́,mo sì ń rọ bíi koríko.

Orin Dafidi 102