Orin Dafidi 102:3-8 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Nítorí ọjọ́ ayé mi ń kọjá lọ bí èéfín,eegun mi gbóná bí iná ààrò.

4. Ìdààmú bá ọkàn mi, mo rọ bíi koríko,tóbẹ́ẹ̀ tí mo gbàgbé láti jẹun.

5. Nítorí igbe ìrora mi,mo rù kan eegun.

6. Mo dàbí igúnnugún inú aṣálẹ̀,àní, bí òwìwí inú ahoro.

7. Mo dùbúlẹ̀ láìlè sùn,mo dàbí ẹyẹ tí ó dá wà lórí òrùlé.

8. Àwọn ọ̀tá ń fi mí ṣe yẹ̀yẹ́ tọ̀sán-tòru,àwọn tí wọn ń pẹ̀gàn mi ń fi orúkọ mi ṣépè.

Orin Dafidi 102