Orin Dafidi 102:18-22 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Kí ẹ kọ èyí sílẹ̀ fún ìran tí ń bọ̀,kí àwọn ọmọ tí a kò tíì bí lè máa yin OLUWA,

19. pé OLUWA bojú wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀,láti ọ̀run ni ó ti bojú wo ayé;

20. láti gbọ́ ìkérora àwọn ìgbèkùn,ati láti dá àwọn tí a dájọ́ ikú fún sílẹ̀.

21. Kí á lè pòkìkí orúkọ OLUWA ní Sioni,kí á sì máa yìn ín lógo ní Jerusalẹmu,

22. nígbà tí àwọn orílẹ̀-èdè bá péjọ tàwọn tọba wọn,láti sin OLUWA.

Orin Dafidi 102