21. “Èyí ni òfin Nasiri, ṣugbọn bí Nasiri kan bá ṣe ìlérí ju ẹbọ tí òfin là sílẹ̀ lọ, ó gbọdọ̀ mú ìlérí náà ṣẹ.”
22. OLUWA sọ fún Mose pé
23. kí ó sọ fún Aaroni ati àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Báyìí ni ẹ óo máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli.
24. ‘Kí OLUWA bukun yín,kí ó sì pa yín mọ́.
25. Kí OLUWA mú kí ojú rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí yín lára,kí ó sì ṣàánú fún yín.
26. Kí OLUWA bojúwò yín,kí ó sì fún yín ní alaafia.’
27. “Bẹ́ẹ̀ ni wọn óo fi orúkọ mi súre fún àwọn ọmọ Israẹli, n óo sì bukun wọn.”